Song of Solomon 2

Olólùfẹ́

1Èmi ni ìtànná Ṣaroni
bí ìtànná lílì àwọn Àfonífojì.
Olólùfẹ́

2Bí ìtànná lílì ní àárín ẹ̀gún
ni olólùfẹ́ mi ní àárín àwọn wúńdíá.
Olólùfẹ́

3Bí igi ápù láàrín àwọn igi inú igbó,
ni olólùfẹ́ mí láàrín àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin
Mo fi ayọ̀ jókòó ní abẹ́ òjìji rẹ̀,
Èso rẹ̀ sì dùn mọ́ mi ní ẹnu.
4Ó mú mi lọ sí ibi gbọ̀ngàn àsè,
ìfẹ́ sì ni ọ̀págun rẹ̀ lórí mi.
5Fi agbára adùn àkàrà dá mi dúró.
Fi èso ápù tù mi lára
nítorí àìsàn ìfẹ́ ń ṣe mí.
6Ọwọ́ òsì rẹ ń bẹ lábẹ́ orí mi
ọwọ́ ọ̀tún rẹ sì ń gbà mí mọ́ra
7Ẹ̀yin ọmọbìnrin Jerusalẹmu,
mo fi abo egbin àti ọmọ àgbọ̀nrín fi yín bú
kí ẹ má ṣe ru ìfẹ́ olùfẹ́ mi sókè
kí ẹ má sì ṣe jí i títí yóò fi wù ú.

8Gbọ́ ohùn olùfẹ́ mi!
Wò ó! Ibí yìí ni ó ń bọ̀.
Òun ń fò lórí àwọn òkè ńlá,
Òun bẹ́ lórí àwọn òkè kéékèèkéé
9Olùfẹ́ mi dàbí abo egbin tàbí ọmọ àgbọ̀nrín
Wò ó! Níbẹ̀ ni ó wà lẹ́yìn ògiri wa
Ó yọjú ní ojú fèrèsé
Ó ń fi ara rẹ̀ hàn lójú fèrèsé ọlọ́nà
10Olùfẹ́ mi fọhùn ó sì sọ fún mi pé,
“Dìde, Olólùfẹ́ mi,
arẹwà mi, kí o sì wà pẹ̀lú mi.
11Wò ó! Ìgbà òtútù ti kọjá;
òjò ti rọ̀ dawọ́, ó sì ti lọ.
12Àwọn òdòdó fi ara hàn lórí ilẹ̀
àsìkò ìkọrin àwọn ẹyẹ dé
a sì gbọ́ ohùn àdàbà ní ilẹ̀ wa.
13Igi ọ̀pọ̀tọ́ mú èso tuntun jáde,
àwọn àjàrà nípa ìtànná wọ́n fún ni ní òórùn dídùn,
Dìde, wá, Olólùfẹ́ mi;
Arẹwà mi nìkan ṣoṣo, wá pẹ̀lú mi.”
Olùfẹ́

14Àdàbà mi wà nínú pàlàpálá òkúta,
ní ibi ìkọ̀kọ̀ ní orí òkè gíga,
fi ojú rẹ hàn mí,
jẹ́ kí èmi gbọ́ ohùn rẹ;
Nítorí tí ohùn rẹ dùn,
tí ojú rẹ sì ní ẹwà.
15Bá wa mú àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀,
àní àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ kéékèèkéé
tí ń ba ọgbà àjàrà jẹ́,
àwọn ọgbà àjàrà wa tó ní ìtànná.
Olólùfẹ́

16Olùfẹ́ mi ni tèmi èmi sì ni tirẹ̀;
Ó ń jẹ láàrín àwọn koríko lílì.
17Títí ìgbà ìtura ọjọ́
títí òjìji yóò fi fò lọ,
yípadà, olùfẹ́ mi,
kí o sì dàbí abo egbin
tàbí ọmọ àgbọ̀nrín
lórí òkè Beteri.
Copyright information for YorBMYO